Ewì Ológundúdú
From Wikipedia
A. S. Oyewale (2003), ‘Ìtúpalè kókó-Òrò Ajemósèlú nínú Ewì Ológundúdú’., Àpilèko fún Oyè Eémeè, DALL, OAU, Ifè, Nigeria.
[edit] Àṣ amọ̀
Àgbéyèwò kókó-òrò ajemósèlú ilè Nàìjíríà gégé bí ó ti se jeyo nínú ewì Ológundúdú ni ó je isé yìí lógún. Àpilèko yìí se òfìntótó ìtàn nípa ìsèlú ilè. Nàìjíríà ní ìbámu pèlú ojú tí akéwì fì wo àwon òrò ìsèlú náà. Èyí wáyé léte àti gbé isé akéwì náà lérí ìwòn àti èròngbà láti mú kí ìwòye wa lè gbòòrò nípa ojú tí a fi ń wo òrò ìsèlú ìgbàlódé ní orílè-èdè Nàìjíríà gégé bí akéwì ti sàgbékalè rè. Fún àpilèko yìí ní pàtó, a se àsàyàn àwon ewì tí Ológundúdú ti ménuba òrò nípa ìsèlú Ìgbéléwòn isé náà dá lórí fífi tíórì ìfojú-èrò-Marx-wo-lítírésò gégé bí i tíórì àmúlò. Isé yìí se àkíyèsí nínú ewì Ológundúdú pé, àwon kókó-òrò tó je mó ìsèlú ilè Nàìjírí lóje akéwì náà lógún jùlo. Fún ìdí èyí, isé àpilèko yìí fihàn pé, àwon akéwì ìgbàlódé Yorùbá ti bèrè síi nawójà won kojá agbo Yorùbá títí dé orílè èdè Nàìjíríà lápapò. Bákan náà, isé ìwádìí yìí fìdí rè múlè pé àwon akéwì Yorùbá kì í se afonrere àwon ìsèlè nìkan sùgbón wón tún jé agbáterù fún àlààfíà àti ètò ìsèjoba tó móyán lórí. Agbéyèwò àwon kókó-òrò inú ewì Ologúndúdú fihàn pé, ohun tó je é lógún jùlo ni láti se ìkìlò fún gbogbo àwon tó ń kópa nínú ìsèlú ìgbàlódé ilè Nàìjíríà láti se pèlé. Ohun tó je é lógún la sàpèjúwe gégé bí i lámèyító tí ewu isé rè dá lórí ojúsàájú síse. Àkíyèsí wa nínú isé Ológundúdú ni wí pé, o máa ń se ojúsàájú, ìdájó àìkógo já, àti sísé àfihàn òduwòn àwon ènìyàn àti ìsèlè láìmímò kíkún nípa won.
Orúko Alábòjúútó: Òmówé A. Akínyemí
Ojú ìwé: 303